BBC News, Yorùbá - Ìròyìn
Ìròyìn tó ṣe kókó
Kì í ṣe pé mi ò nífẹ̀ẹ́ PDP, ìdí tí mo fi kúrò níbẹ̀ rèé - Gómìnà Adeleke
Nigba to n ṣalaye idi rẹ to ṣe fi PDP silẹ lẹyin to ti figba kan leri pe oun ko ni i kuro ninu ẹgbẹ ọhun, Adeleke sọ pe oun nifẹẹ PDP, ṣugbọn ohun to yẹ foun ni lati kuro nibẹ lasiko yii.
Remi Tinubu ati Adeleke fèsì lórí ìsẹ̀lẹ̀ tó wáyé n'Ile Ife
Ẹ o ranti pe iyawo aarẹ ilẹ wa, Oluremi Tinubu, lo ni oun fun Gomina ipinlẹ naa, Ademola Adeleke, ni iṣẹju marun-un lati sọrọ, ko si dakẹ orin to n kọ nita gbangba.
Àlàyé rèé bí àṣírí ṣe tú nípa ọkùnrin kan tó lúgọ sábẹ́ táyà bàálù ní pápákọ̀ òfurufú Ilorin pẹ̀lú èròńgbà láti jápa lọ Amẹrika
Iṣẹlẹ yii n fi han pe awọn ẹṣọ alaabo papako ofurufu ko ṣiṣẹ wọn to bii iṣẹ ni ọkunrin yii fi ri aye wọ ibi ti ko yẹ ko de.
Ọkọ̀ ńlá kọlù mọ́to mẹ́ta lọ́nà márosẹ̀ Ibadan sí Eko, bàbá, ìyá àti ọmọ wọn kú, èèyàn méjì míì farapa
Àjọ tó ń mójútó ojú pópó ní ìpínlẹ̀ Eko, Lagos State Traffic Management Authority, LASTMA, nínú àtẹ̀jáde kan sọ pé òwúrọ̀ ọjọ́rú ni ìjàmbá náà wáyé.
Ipa wo ni ìgbésẹ̀ Tinubu láti kó ọmọ ogun lọ Benin yóò ní lórí ìgbógun ti agbébọn ní Naijiria?
Erongba Aarẹ Tinubu ni lati ko ọmogun ranṣẹ si orilẹede naa lati le jẹ ki alaafia jọba nibẹ lẹyin tawọn ọmogun ọlọtẹ fẹ ditẹ gbajọba Aarẹ Patrice Talon lọjọ Aiku to kọja.
Wo àwọn gómìnà PDP tó ti fi ẹgbẹ́ sílẹ̀ àti àwọn tó ṣẹ́kù
Lanaa ode yii ni awọn gomina meji, Ademola Adeleke, ti ipinlẹ Osun, ati Siminalayi Fubara, ti ipinlẹ Rivers tun fi PDP silẹ, ti wọn gba ẹgbẹ miran lọ.
Ilé aṣòfin ní kí Tinubu fi ọmọ ogun ránṣẹ́ sí Benin Republic
Aarọ ọjọ Aiku naa ni iroyin gbode, pe awọn ologun kan ti gba ijọba lorilẹede Benin, wọn si ti le Aarẹ Patrince Talon lọ raurau amọ ti ete iditẹgbajọba naa fori sanpọn.
Kí ni ìdìtẹ̀gbàjọba ọmogun ọlọ̀tẹ̀ tó forí ṣánpọ́n ní Benin Republic túmọ̀ sí fún ilẹ̀ náà àti Áfíríkà?
Onimọ nipa eto iṣejọba, Ọmọwe Jude Mutah, sọ pe awọn nnkan to n ṣẹlẹ kaakiri orilẹede Benin le jẹ ohun to ṣokunfa igbiyanju awọn ọmogun ọlọtẹ lati ditẹ gbajọba Aarẹ Talon.
Orin, Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́, Duration 0,57
Kò ṣeé má gbọ̀ọ́
Ṣé a lè fòfin de ọmọdé láti lo ojú òpó ayélujára, ọjọ́ orí wo ló yẹ́ kí ọmọdé bẹ̀rẹ̀ lílò rẹ̀?
Lati ọjọ kẹwaa oṣu Kejila, awọn ọmọde ti ọjọ ori wọn ko to mẹrindinlogun (16) lorilẹede Australia ko ni i le maa lo oju opo ayelujara mọ.
Fídíò, "Òbí mi gbé mi sálọ sílé ọkọ tí ń kò mọ̀ tẹ́lẹ̀ àmọ́ a ti lo ọdún 48 pọ̀ nínú ìgbéyàwó, ojú rí tó", Duration 6,06
BBC News Yorùbá Maria àti Amos Adejinmi, tí wọn ṣe ìgbeyàwó Àṣàǹte láti ọdún méjìdínláàdọ́ta sọ̀rọ̀, wọ́n sọ bí ìgbeyàwó aláìfojúríraẹ́ni náà ṣe wáyé àti ohun tí ojú wọn rí.
Human Rights Day: Wo àwọn ẹ̀tọ́ rẹ lábẹ́ òfin àtàwọn ọ̀nà tí wọn ń gbà tẹ ẹ̀tọ́ rẹ̀ mọ́lẹ̀
Ní òní tíí ṣe àyájọ́ ọjọ́ ọmọnìyàn ní àgbáyé, BBC News Yorùbá ṣe àkójọpọ̀ ìròyìn nípa ohun tí ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn túmọ̀ sí lábẹ́ òfin àti àwọn ọ̀nà tí wọ̀n ń gbà tẹ ẹ̀tọ́ rẹ lójú.
BBC News Yorùbá ti wà lórí ìkànnì WhatsApp
Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ
Ìròyìn Àkàgbádùn
Kí nídìí táwọn Ajẹ́rìí Jèhófà kìí fí gba ẹ̀jẹ̀ bí obìnrin tó ní àìsàn jẹjẹrẹ ṣe kọ̀ láti gba ẹ̀jẹ̀
Auntie Esther tó gbajúmọ̀ lórí ìkànnì X látàrí iṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú bí ó ṣe máa ń bá àwọn èèyàn ra oúnjẹ tútù kàn sójú òpó náà nínú oṣù Kọkànlá láti bèèrè fún ìrànlọ́wọ́ nítorí àìsàn jẹjẹrẹ ọyàn tó ní.
Olubadan Rashidi Ladoja figbe ta, ṣàlàyé ìdí tó fi nira láti dupò Ọba mú, ju ipò Gómìnà lọ, pé fún ṣíṣí àwọn bodè Nàíjíríà
Ọba Rashidi Ladoja to ti figba kan ri jẹ gomina ipinlẹ Oyo, ṣalaye pe gomina lagbara lati paṣẹ gẹgẹ bii olori ijọba, amọ, ọba ko ni iru agbara bẹẹ.
Ohun ìyanu rere ń bọ̀ nínu ìjọba Tinubu, gbogbo ọ̀tá rẹ̀ ni ojú yóò tì - Remi Tinubu
Lara awọn èèkànlú to péjú síbi ayẹyẹ naa ni aya ààrẹ orílẹ̀èdè Naijiria, Oluremi Tinubu àti ààrẹ àná, Oloye Olusegun Obasanjo.
Láti ìgbà tí wọ́n ti jí Ọba wa gbé lọ, ọlọ́pàá kò dá sí wa, àwa nìkan là ń sá kiri, ìjọba Kwara, ẹ gbà wá – Mọ̀lẹ̀bí Ọba tí wọ́n jí gbé
Ninu atẹajade kan ti mọlẹbi kabiesi, eyii ti agbẹnusọ rẹ, Alhaji Rafiu Ayinla Lawal fi lede, ni wọn ti ke gbajare bẹẹ.
Wo gbogbo ohun to yẹ kí o mọ̀ nípa ìdíje Afcon 2025
BBC ṣe atupalẹ gbogbo nnkan to yẹ ki o mọ nipa idije Afcon 2025 tii ṣe ẹlẹẹkarundinloji iru rẹ ninu iroyin yii.
Ìjọba àpapọ̀ kéde ìdáǹdè akẹ́kọ̀ọ́ 100 nínú àwọn tí wọ́n jí gbé ní St Mary Catholic, Papiri
Ọjọ Aiku ana ni iroyin naa gbode kari ayelujara, pe ijọba apapọ ti ri ọgọrun-un akẹkọọ gba kalẹ loko ajinigbe ninu awọn ti ajinigbe gbe lọ nile ẹkọ naa.
"Wọ́n pa bàbá-bàbá mi àti bàbá ìyàwó mi, bó ṣe wù wọ́n ni wọn ǹ pa wa, n kò fẹ́ kí wọn fi okùn fún mi lọ́rùn pa, wọ̀n fẹ́ pa aláwọ̀ funfun rẹ́ ní South Africa"
Ẹka BBC Africa tó ń tan iná ìwádìí finmúfínlẹ̀ nípa ẹ̀sùn báwọn aláwọ̀ dúdú ṣe ń pàwọn àgbẹ̀ aláwọ̀ funfun nílẹ̀ South Africa, àbọ̀ wa rèé.
Ìdìtẹ̀gbàjọba mẹ́wàá tó ti wáyé ní Afrika láàárín ọdun márùn ún sẹ́yìn
Laarin ọdun marun un si asiko yii, o kere tan, iṣẹlẹ iditẹgbajọba mẹsan an ọtọto lo ti waye nilẹ Afrika, bo ṣe jẹ ree.
Agbébọn tún kọlu ilé ìjọ́sìn, wọ́n pa ìyàwó pásítọ̀, jó ọ̀pọ̀ ọkọ̀ níná, ṣe ọ̀pọ̀ èèyàn lèṣe
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ Àìkú, ọjọ́ Keje, oṣù Kejìlá, ọdún 2025 lásìkò tí ìjọ́sìn ń lọ lọ́wọ́ ni ìkọlù ọ̀hún wáyé gẹ́gẹ́ bí àtẹ̀jáde kan tí agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Anambra, Tochukwu Ikenga ṣẹ sọ.
Agbègbè méjì dojú ogun kọra wọn, ẹ̀mí bọ́, ọ̀pọ̀ dúkìá ṣòfò, ìjọba kéde òfin kónílé-gbélé
Tẹ o ba gbagbe, ṣaaju ni ikọlu to jọ mọ ẹlẹyamẹya ti n waye lawọn agbegbe naa, to si fa rogbodiyan to pọ.
Àlàyé rèé lórí ìdí tí wọn ṣe lé odidi ọba, ẹni ọdún 37 kúrò láàrin ìlu, gbẹ́sẹ̀ lé ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́ rẹ̀
Fidio kan to gba ori ayelujara kan wa se afihan bi oriade naa se kuro ninu ilu ọhun pẹlu idojuti nla, tawọn agbofinro si sin lọwọọwọ pẹlu rẹ.
Àwọn ipa tí ìgbésẹ̀ mímú ológun mọ̀kànlá sáhàámọ́, gbẹ́sẹ́ lé bàálù le è ní bí Nàíjíríà ṣe fèsì lórí ìdí tí bàálù rẹ̀ fi balẹ̀ lójijì ní agbègbè Sahel
Lasiko ti awọn Ologun naa duro lojiji nilu Bobo-Dioulasso, tii se ilu to tobi sikeji nilẹ Burkina Faso, ni wọn gbe igbesẹ naa.
Ìròyìn Pàtàkì
Kọ́milẹ́kọ̀ọ́
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Ìjọba gbọ́dọ̀ ní àkójọpọ̀ orúkọ gbogbo aráàlú lórí ẹ̀rọ kọ̀mpútà tó bá fẹ́ rẹ́yìn ìgbésùnmọ̀mí - Christopher Musa
Ninu lẹta ti Tinubu fi ṣọwọ si aarẹ ile aṣofin agba l'Abuja, Sẹnẹtọ Godswill Akpabio, fun ibuwọlu ni aarẹ ti ṣalaye pe Musa ni yoo rọpo Alhaji Mohammed Badaru Abubakar minisita eto aabo tẹlẹ to kọwe fipo silẹ lọjọ Aje.
Àwọn afurasí tọ́wọ́ tẹ̀ ṣàlàyé bí wọ́n ṣe pa òṣìṣẹ́ FRSC àti ọmọ rẹ̀ tí wọ́n jí gbé l'Ogun
Ẹni ọdun mejidinlogoji ni wọn pe Lasisi Oluwamayokun, nigba ti ọmọ rẹ, Lasisi Sewa jẹ ọmọ ọdun mejila.
'Ifá kọ́ la fi n yan Awujale ilẹ̀ Ìjẹ̀bú, bá ṣe n ṣe rèé'
Alaye lori bi wọn ṣe n yan Awujalẹ ilẹ Ijẹbu.
Lóòótọ́ ni mi ò kí ń dárúkọ Jesu nínú orin mi, Jesu kò ní ká polongo òun – Sola Allyson
Allyson lo sọ ọrọ naa ninu ifọrọwerọ kan pẹlu ileeṣẹ agbohunsafẹfẹ ori ayelujara, Oyinmomo TV.
Ariwo gbòde pé Wasiu Ayinde kì í ṣe ọmọ ìdílé Fusengbuwa tó pe ara rẹ̀, KWAM 1 gbé ẹ̀rí kalẹ̀
Ẹ o ranti pe lọjọ kẹta, oṣu Kejila ọdun 2025 ni K1 kọ lẹta si idile Fusengbuwa ti yoo fa Awujalẹ tuntun kalẹ, pẹlu alaye pe ọmọ idile naa ni oun, lati iran Jadiara.
Sheikh Adam Al-Ilory àti Sheikh Muyideen Bello: Àwọn àgbàọjẹ̀ àáfà tí wọn ti kú àmọ́ tí iṣẹ́ wọn ṣì ń dáhùn nílẹ̀ Yorùbá
Awọn musulumi to fi mọ awọn ẹlẹsin Kristẹni ko le gbagbe iru awọn aafa bẹẹ fun ipa ribi ribi ti wọn ti ko ninu igbelarugẹ ẹsin Islam.
Ṣé ebi máa ń pa ọ́ tí o bá ń ṣe wàhálà lápọ̀jù? Ọ̀nà àbáyọ rèé
Ti a ba ṣe wahala laṣeju, o le maa jẹ ka maa ṣafẹri awọn ounjẹ didun bii chocolate ati pizza tabi ki ounjẹ ma tilẹ wu wa jẹ.
Kí ló dé tí APC yọ Omisore, Omoworare àtàwọn mí-ìn kúrò nínú ìbò abẹ́lé sípò gómìnà Osun?
Yatọ si Omisore, awọn mi-in ti APC tun fofin de ni Senetọ Babajide Omoworare, Kunle Adegoke (SAN), Akin Ogunbiyi, Benedict Olugboyega Alabi toun naa ti figba kan jẹ igbakeji gomina, Dotun Babayemi ati Babatunde Haketer Oralusi.































































